Wednesday, March 27
Ẹ máa wá Ìjọba náà . . . lákọ̀ọ́kọ́.—Mát. 6:33.
Nígbà tí Jésù kú, inú àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ bà jẹ́ gan-an. Yàtọ̀ sí pé ọ̀rẹ́ wọn ti kú, ṣe ló tún ń ṣe wọ́n bíi pé wọn ò nírètí mọ́. (Lúùkù 24:17-21) Àmọ́ nígbà tí Jésù fara hàn wọ́n, ó fara balẹ̀ ṣàlàyé ìdí tóun fi gbọ́dọ̀ jìyà kóun sì kú àti báwọn nǹkan yẹn ṣe ń mú àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì ṣẹ. Yàtọ̀ síyẹn, ó tún gbé iṣẹ́ pàtàkì kan fún wọn. (Lúùkù 24:26, 27, 45-48) Nígbà tí Jésù fi máa pa dà sọ́run, ẹkún àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ ti dayọ̀. Ìdí sì ni pé wọ́n mọ̀ pé Ọ̀gá àwọn ti jíǹde, ó sì máa ran àwọn lọ́wọ́ láti ṣe iṣẹ́ náà yanjú. Torí náà, ayọ̀ tí wọ́n ní yìí ń jẹ́ kí wọ́n yin Jèhófà, wọn ò sì jẹ́ kí iṣẹ́ ìwàásù sú wọn. (Lúùkù 24:52, 53; Ìṣe 5:42) Ká lè fara wé àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù, ó máa gba pé ká fi Ìjọba Ọlọ́run sípò àkọ́kọ́ nígbèésí ayé wa. Lóòótọ́, ó yẹ ká ní ìfaradà ká tó lè máa sin Jèhófà nìṣó, àmọ́ Jèhófà ti ṣèlérí fún wa pé òun máa bù kún wa gan-an tá a bá ṣe bẹ́ẹ̀.—Òwe 10:22. w23.01 30-31 ¶15-16
Bíbélì kíkà nígbà Ìrántí Ikú Kristi: (Ohun tó ṣẹlẹ̀ lójú mọmọ: Nísàn 16) Máàkù 16:2-8
Thursday, March 28
Ìwọ yóò sì pa dà sí erùpẹ̀.—Jẹ́n. 3:19.
A ò ní fẹ́ ṣe àṣìṣe tí Ádámù àti Éfà ṣe. Tá ò bá fẹ́ kí irú ẹ̀ ṣẹlẹ̀ sí wa, a gbọ́dọ̀ máa kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà, ká mọyì àwọn ànímọ́ rẹ̀, ká sì máa ronú lọ́nà tó ń gbà ronú. Tá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, ìfẹ́ tá a ní fún Jèhófà á túbọ̀ máa lágbára sí i. Ẹ jẹ́ ká gbé àpẹẹrẹ Ábúráhámù yẹ̀ wò. Ó nífẹ̀ẹ́ Jèhófà gan-an. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé láwọn ìgbà kan, ó ṣòro fún un láti mọ ìdí tí Jèhófà fi ṣe àwọn ìpinnu kan, Ábúráhámù ò torí ìyẹn kẹ̀yìn sí Jèhófà. Dípò bẹ́ẹ̀, ṣe ló gbìyànjú láti túbọ̀ mọ ẹni tí Jèhófà jẹ́. Bí àpẹẹrẹ, nígbà tó gbọ́ pé Jèhófà fẹ́ pa Sódómù àti Gòmórà run, Ábúráhámù kọ́kọ́ rò pé “Onídàájọ́ gbogbo ayé” máa pa àwọn èèyàn burúkú pa pọ̀ pẹ̀lú àwọn olódodo. Ábúráhámù gbà pé Jèhófà ò ní ṣe irú ẹ̀ láé, torí náà ó fìrẹ̀lẹ̀ bi Jèhófà láwọn ìbéèrè kan, Jèhófà náà sì fi sùúrù dá a lóhùn. Nígbẹ̀yìn-gbẹ́yín, Ábúráhámù rí i pé Jèhófà máa ń ṣàyẹ̀wò ọkàn gbogbo àwa èèyàn, kì í sì í fìyà jẹ àwọn aláìṣẹ̀ pa pọ̀ pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.—Jẹ́n. 18:20-32. w22.08 28 ¶9-10
Friday, March 29
Ẹni tó ṣeé fọkàn tán máa ń pa àṣírí mọ́.—Òwe 11:13.
Lọ́dún 455 Ṣ.S.K., lẹ́yìn tí Gómìnà Nehemáyà tún àwọn ògiri Jerúsálẹ́mù kọ́, ó wá àwọn ọkùnrin tó ṣeé fọkàn tán kí wọ́n lè máa bójú tó ìlú náà. Nehemáyà wá yan Hananáyà lára àwọn ọkùnrin náà pé kó jẹ́ olórí Ibi Ààbò. Bíbélì sọ pé Hananáyà ló “ṣeé fọkàn tán jù lọ, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run tòótọ́ ju ọ̀pọ̀ àwọn míì lọ.” (Neh. 7:2) Hananáyà fọwọ́ pàtàkì mú gbogbo iṣẹ́ tí wọ́n yàn fún un torí pé ó nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, kò sì fẹ́ ṣe ohun tí inú ẹ̀ ò dùn sí. Táwa náà bá nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, tá ò sì ṣe ohun tó máa bà á nínú jẹ́, àwọn èèyàn máa fọkàn tán wa nínú iṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run tá à ń ṣe. Àpẹẹrẹ ẹlòmíì ni Tíkíkù. Òun àti àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù jọ ṣiṣẹ́, Pọ́ọ̀lù sì fọkàn tán an. Tíkíkù máa ń ràn án lọ́wọ́ torí Pọ́ọ̀lù pè é ní “òjíṣẹ́ olóòótọ́.” (Éfé. 6:21, 22) Pọ́ọ̀lù fọkàn tán an pé kì í ṣe pé ó kàn máa fi àwọn lẹ́tà òun jíṣẹ́ fáwọn ará ní Éfésù àti Kólósè nìkan, ó tún máa gbà wọ́n níyànjú, á sì tù wọ́n nínú. Àpẹẹrẹ Tíkíkù jẹ́ ká rántí àwọn ọkùnrin olóòótọ́ tó ṣeé fọkàn tán, tí wọ́n ń ràn wá lọ́wọ́ lónìí láti sún mọ́ Jèhófà.—Kól. 4:7-9. w22.09 9-10 ¶5-6