Thursday, March 28
Ìwọ yóò sì pa dà sí erùpẹ̀.—Jẹ́n. 3:19.
A ò ní fẹ́ ṣe àṣìṣe tí Ádámù àti Éfà ṣe. Tá ò bá fẹ́ kí irú ẹ̀ ṣẹlẹ̀ sí wa, a gbọ́dọ̀ máa kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà, ká mọyì àwọn ànímọ́ rẹ̀, ká sì máa ronú lọ́nà tó ń gbà ronú. Tá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, ìfẹ́ tá a ní fún Jèhófà á túbọ̀ máa lágbára sí i. Ẹ jẹ́ ká gbé àpẹẹrẹ Ábúráhámù yẹ̀ wò. Ó nífẹ̀ẹ́ Jèhófà gan-an. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé láwọn ìgbà kan, ó ṣòro fún un láti mọ ìdí tí Jèhófà fi ṣe àwọn ìpinnu kan, Ábúráhámù ò torí ìyẹn kẹ̀yìn sí Jèhófà. Dípò bẹ́ẹ̀, ṣe ló gbìyànjú láti túbọ̀ mọ ẹni tí Jèhófà jẹ́. Bí àpẹẹrẹ, nígbà tó gbọ́ pé Jèhófà fẹ́ pa Sódómù àti Gòmórà run, Ábúráhámù kọ́kọ́ rò pé “Onídàájọ́ gbogbo ayé” máa pa àwọn èèyàn burúkú pa pọ̀ pẹ̀lú àwọn olódodo. Ábúráhámù gbà pé Jèhófà ò ní ṣe irú ẹ̀ láé, torí náà ó fìrẹ̀lẹ̀ bi Jèhófà láwọn ìbéèrè kan, Jèhófà náà sì fi sùúrù dá a lóhùn. Nígbẹ̀yìn-gbẹ́yín, Ábúráhámù rí i pé Jèhófà máa ń ṣàyẹ̀wò ọkàn gbogbo àwa èèyàn, kì í sì í fìyà jẹ àwọn aláìṣẹ̀ pa pọ̀ pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.—Jẹ́n. 18:20-32. w22.08 28 ¶9-10
Friday, March 29
Ẹni tó ṣeé fọkàn tán máa ń pa àṣírí mọ́.—Òwe 11:13.
Lọ́dún 455 Ṣ.S.K., lẹ́yìn tí Gómìnà Nehemáyà tún àwọn ògiri Jerúsálẹ́mù kọ́, ó wá àwọn ọkùnrin tó ṣeé fọkàn tán kí wọ́n lè máa bójú tó ìlú náà. Nehemáyà wá yan Hananáyà lára àwọn ọkùnrin náà pé kó jẹ́ olórí Ibi Ààbò. Bíbélì sọ pé Hananáyà ló “ṣeé fọkàn tán jù lọ, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run tòótọ́ ju ọ̀pọ̀ àwọn míì lọ.” (Neh. 7:2) Hananáyà fọwọ́ pàtàkì mú gbogbo iṣẹ́ tí wọ́n yàn fún un torí pé ó nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, kò sì fẹ́ ṣe ohun tí inú ẹ̀ ò dùn sí. Táwa náà bá nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, tá ò sì ṣe ohun tó máa bà á nínú jẹ́, àwọn èèyàn máa fọkàn tán wa nínú iṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run tá à ń ṣe. Àpẹẹrẹ ẹlòmíì ni Tíkíkù. Òun àti àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù jọ ṣiṣẹ́, Pọ́ọ̀lù sì fọkàn tán an. Tíkíkù máa ń ràn án lọ́wọ́ torí Pọ́ọ̀lù pè é ní “òjíṣẹ́ olóòótọ́.” (Éfé. 6:21, 22) Pọ́ọ̀lù fọkàn tán an pé kì í ṣe pé ó kàn máa fi àwọn lẹ́tà òun jíṣẹ́ fáwọn ará ní Éfésù àti Kólósè nìkan, ó tún máa gbà wọ́n níyànjú, á sì tù wọ́n nínú. Àpẹẹrẹ Tíkíkù jẹ́ ká rántí àwọn ọkùnrin olóòótọ́ tó ṣeé fọkàn tán, tí wọ́n ń ràn wá lọ́wọ́ lónìí láti sún mọ́ Jèhófà.—Kól. 4:7-9. w22.09 9-10 ¶5-6
Saturday, March 30
Ìfẹ́ máa ń bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.—1 Pét. 4:8.
Jósẹ́fù dojú kọ àwọn ìṣòro tó le gan-an fún nǹkan bí ọdún mẹ́tàlá (13). Jósẹ́fù tiẹ̀ lè bẹ̀rẹ̀ sí í ronú pé ṣé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ òun ṣá. Ó sì lè máa rò pé Jèhófà ti pa òun tì lásìkò tó yẹ kó ran òun lọ́wọ́. Àmọ́ Jósẹ́fù ò ronú bẹ́ẹ̀. Dípò bẹ́ẹ̀, ó fara balẹ̀, ó sì ronú lọ́nà tó tọ́. Kódà, nígbà tó láǹfààní láti gbẹ̀san lára àwọn ẹ̀gbọ́n ẹ̀, kò ṣe bẹ́ẹ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, ṣe ló fìfẹ́ hàn sí wọn, tó sì dárí jì wọ́n. (Jẹ́n. 45:4, 5) Ohun tó ran Jósẹ́fù lọ́wọ́ tó fi lè ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé ó ronú lọ́nà tó tọ́. Dípò kó máa ronú ṣáá nípa ohun táwọn ẹ̀gbọ́n ẹ̀ ṣe sí i, ohun tí Jèhófà fẹ́ kó ṣe ló gbájú mọ́. (Jẹ́n. 50:19-21) Kí la rí kọ́? Tí wọ́n bá ṣe nǹkan tí ò dáa sí ẹ, má bínú sí Jèhófà tàbí kó o máa rò pé Jèhófà ti pa ẹ́ tì. Máa ronú nípa bí Jèhófà ṣe ń ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti fara da ìṣòro náà. Yàtọ̀ síyẹn, táwọn èèyàn bá ṣe ohun tí ò dáa sí ẹ, má wo àìpé wọn, ṣe ni kó o máa fìfẹ́ hàn sí wọn. w22.11 21 ¶4