Saturday, August 29
Máa wádìí dájú àwọn ohun tó ṣe pàtàkì jù.—Fílí. 1:10.
Ká sọ pé ò ń wá iṣẹ́ tó o máa fi bójú tó ìdílé ẹ. Kò pẹ́ sígbà yẹn lo ríṣẹ́ síbi méjì. Kí ló yẹ kó o ṣe? Ó yẹ kó o ronú nípa ohun tí iṣẹ́ kọ̀ọ̀kan máa gbà, bó ṣe jìnnà sílé tó, iye ọjọ́ àti wákàtí tí wàá fi máa ṣiṣẹ́ àtàwọn nǹkan míì. Ká sọ pé o wá rí i pé iṣẹ́ méjèèjì ni Kristẹni lè ṣe ńkọ́? Àmọ́, ọ̀kan wù ẹ́ torí pé o nífẹ̀ẹ́ iṣẹ́ náà tàbí torí pé owó tí wọ́n máa san fún ẹ ju ti ìkejì lọ. Tó bá rí bẹ́ẹ̀, àwọn nǹkan míì wo ló yẹ kó o ronú nípa ẹ̀ kó o tó ṣèpinnu? O lè bi ara ẹ pé: Ṣé iṣẹ́ náà á jẹ́ kí n máa ráyè wá sípàdé? Ṣé á jẹ́ kí n máa wà pẹ̀lú ìdílé mi, kí n sì tún máa bójú tó wọn kí wọ́n lè ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà? Tó o bá bi ara ẹ láwọn ìbéèrè yìí, “àwọn ohun tó ṣe pàtàkì jù,” ìyẹn ìjọsìn Jèhófà àti ìdílé ẹ ni wàá fi ṣáájú àwọn nǹkan tara. Ó sì dájú pé ìpinnu tó máa múnú Jèhófà dùn lo máa ṣe. w25.01 17 ¶11-13
Sunday, August 30
Jèhófà wà nítòsí àwọn tó ní ọgbẹ́ ọkàn.—Sm. 34:18.
Táwọn èèyàn bá ti hùwà ìkà sí ẹ rí, mọ̀ dájú pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ ẹ, o sì ṣeyebíye lójú ẹ̀. Tí “àárẹ̀ bá [bá] ẹ̀mí” ẹ, máa rántí pé Jèhófà rí ohun rere kan lọ́kàn ẹ, ìdí nìyẹn tó fi fà ẹ́ sọ́dọ̀ ara ẹ̀. (Jòh. 6:44) Kò sígbà tí ò ṣe tán láti ràn ẹ́ lọ́wọ́ torí pé o ṣeyebíye lójú ẹ̀. Tá a bá wo àpẹẹrẹ Jésù, a máa mọ bí ọ̀rọ̀ ṣe máa ń rí lára Jèhófà. Nígbà tí Jésù ń wàásù láyé, ó kíyè sí àwọn tí wọ́n ń fojú àbùkù wò, ó sì ṣàánú wọn. (Mát. 9:9-12) Nígbà tí obìnrin kan tó ń ṣàìsàn tó le gan-an fọwọ́ kan aṣọ Jésù, ó mọ̀ pé ara òun máa yá, torí náà Jésù tù ú nínú, ó sì gbóríyìn fún un torí pé ó nígbàgbọ́. (Máàkù 5:25-34) Ohun tí Jésù ṣe yìí fi hàn pé ó fìwà jọ Bàbá ẹ̀ láìkù síbì kan. (Jòh. 14:9) Torí náà, mọ̀ dájú pé Jèhófà mọyì ẹ, ó sì ń kíyè sí àwọn ìwà rere tó o ní, ìgbàgbọ́ tó o ní àti bó o ṣe nífẹ̀ẹ́ ẹ̀. w24.10 7 ¶4-5
Monday, August 31
Gba omijé mi sínú ìgò awọ rẹ.—Sm. 56:8.
Nígbà ayé Dáfídì, ọ̀pọ̀ ìṣòro ló ní tó mú kó sunkún. Àwọn èèyàn kórìíra ẹ̀, kódà àwọn ará ilé ẹ̀ àtàwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ kan dalẹ̀ ẹ̀. (1 Sám. 19:10, 11; 2 Sám. 15:10-14, 30) Nígbà kan, ó sọ pé: “Àárẹ̀ ti mú mi nítorí ẹ̀dùn ọkàn mi; láti òru mọ́jú ni omijé mi ń rin ibùsùn mi gbingbin; ẹkún mi ti fi omi kún àga tìmùtìmù mi.” (Sm. 6:6) Láìka gbogbo ìṣòro tí Dáfídì ní sí, ó dá a lójú pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ òun. Ó sọ pé: “Jèhófà yóò gbọ́ igbe ẹkún mi.” (Sm. 6:8) Ọ̀rọ̀ ẹsẹ ojúmọ́ wa tòní jẹ́ ká rí i pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ wa gan-an, ó sì mọ bọ́rọ̀ ṣe máa ń rí lára wa. Ohun tí Dáfídì ń sọ ni pé ńṣe ló dà bí ìgbà tí Jèhófà ń gba omijé ẹ̀ sínú ìgò kan tàbí tó ń kọ ohun tó ṣẹlẹ̀ sí i sínú ìwé kan. Ó dá Dáfídì lójú pé Jèhófà rí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ sóun, ó sì mọ ẹ̀dùn ọkàn òun. Dáfídì mọ̀ pé kì í ṣe pé Jèhófà mọ gbogbo nǹkan tójú òun ti rí nìkan ni, ó tún mọ bó ṣe rí lára òun. w24.12 22 ¶11-12