Friday, August 28
O ṣí ọwọ́ rẹ, o sì fún gbogbo ohun alààyè ní ohun tí wọ́n ń fẹ́.—Sm. 145:16.
Tá a bá ń fún àwọn èèyàn ní nǹkan, Jèhófà là ń fara wé, ìyẹn sì máa fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ wọn. Bí àpẹẹrẹ, ṣé o mọ ẹnì kan tá a jọ ń sin Jèhófà tó nílò oúnjẹ tàbí aṣọ? Jèhófà lè lò ẹ́ láti fún ẹni náà lóhun tó nílò. Àwa èèyàn Jèhófà máa ń ran ara wa lọ́wọ́ nígbà tí àjálù bá ṣẹlẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, nígbà àjàkálẹ̀ àrùn kòrónà, àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin fún àwọn ará lóúnjẹ, aṣọ àtàwọn nǹkan míì tí wọ́n nílò. Ọ̀pọ̀ àwọn ará tún fi owó ṣètìlẹ́yìn fún iṣẹ́ tá à ń ṣe kárí ayé. Ìyẹn jẹ́ ká rówó ṣèrànwọ́ fáwọn ará tí àjálù dé bá. Torí náà, wọ́n ṣe ohun tó wà ní Hébérù 13:16 tó sọ pé: “Ẹ má gbàgbé láti máa ṣe rere, kí ẹ sì máa pín ohun tí ẹ ní pẹ̀lú àwọn ẹlòmíì, torí inú Ọlọ́run máa ń dùn gan-an sí irú àwọn ẹbọ bẹ́ẹ̀.” w24.09 27 ¶6-7
Saturday, August 29
Máa wádìí dájú àwọn ohun tó ṣe pàtàkì jù.—Fílí. 1:10.
Ká sọ pé ò ń wá iṣẹ́ tó o máa fi bójú tó ìdílé ẹ. Kò pẹ́ sígbà yẹn lo ríṣẹ́ síbi méjì. Kí ló yẹ kó o ṣe? Ó yẹ kó o ronú nípa ohun tí iṣẹ́ kọ̀ọ̀kan máa gbà, bó ṣe jìnnà sílé tó, iye ọjọ́ àti wákàtí tí wàá fi máa ṣiṣẹ́ àtàwọn nǹkan míì. Ká sọ pé o wá rí i pé iṣẹ́ méjèèjì ni Kristẹni lè ṣe ńkọ́? Àmọ́, ọ̀kan wù ẹ́ torí pé o nífẹ̀ẹ́ iṣẹ́ náà tàbí torí pé owó tí wọ́n máa san fún ẹ ju ti ìkejì lọ. Tó bá rí bẹ́ẹ̀, àwọn nǹkan míì wo ló yẹ kó o ronú nípa ẹ̀ kó o tó ṣèpinnu? O lè bi ara ẹ pé: Ṣé iṣẹ́ náà á jẹ́ kí n máa ráyè wá sípàdé? Ṣé á jẹ́ kí n máa wà pẹ̀lú ìdílé mi, kí n sì tún máa bójú tó wọn kí wọ́n lè ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà? Tó o bá bi ara ẹ láwọn ìbéèrè yìí, “àwọn ohun tó ṣe pàtàkì jù,” ìyẹn ìjọsìn Jèhófà àti ìdílé ẹ ni wàá fi ṣáájú àwọn nǹkan tara. Ó sì dájú pé ìpinnu tó máa múnú Jèhófà dùn lo máa ṣe. w25.01 17 ¶11-13
Sunday, August 30
Jèhófà wà nítòsí àwọn tó ní ọgbẹ́ ọkàn.—Sm. 34:18.
Táwọn èèyàn bá ti hùwà ìkà sí ẹ rí, mọ̀ dájú pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ ẹ, o sì ṣeyebíye lójú ẹ̀. Tí “àárẹ̀ bá [bá] ẹ̀mí” ẹ, máa rántí pé Jèhófà rí ohun rere kan lọ́kàn ẹ, ìdí nìyẹn tó fi fà ẹ́ sọ́dọ̀ ara ẹ̀. (Jòh. 6:44) Kò sígbà tí ò ṣe tán láti ràn ẹ́ lọ́wọ́ torí pé o ṣeyebíye lójú ẹ̀. Tá a bá wo àpẹẹrẹ Jésù, a máa mọ bí ọ̀rọ̀ ṣe máa ń rí lára Jèhófà. Nígbà tí Jésù ń wàásù láyé, ó kíyè sí àwọn tí wọ́n ń fojú àbùkù wò, ó sì ṣàánú wọn. (Mát. 9:9-12) Nígbà tí obìnrin kan tó ń ṣàìsàn tó le gan-an fọwọ́ kan aṣọ Jésù, ó mọ̀ pé ara òun máa yá, torí náà Jésù tù ú nínú, ó sì gbóríyìn fún un torí pé ó nígbàgbọ́. (Máàkù 5:25-34) Ohun tí Jésù ṣe yìí fi hàn pé ó fìwà jọ Bàbá ẹ̀ láìkù síbì kan. (Jòh. 14:9) Torí náà, mọ̀ dájú pé Jèhófà mọyì ẹ, ó sì ń kíyè sí àwọn ìwà rere tó o ní, ìgbàgbọ́ tó o ní àti bó o ṣe nífẹ̀ẹ́ ẹ̀. w24.10 7 ¶4-5