ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Monday, June 9

Ẹni tó bá fara dà á dé òpin máa rí ìgbàlà.—Mát. 24:13.

Ká tó lè rí ìyè àìnípẹ̀kun, ó ṣe pàtàkì pé ká máa ní sùúrù. Bíi tàwọn olóòótọ́ ìránṣẹ́ Jèhófà ìgbà àtijọ́, ó ṣe pàtàkì káwa náà máa ní sùúrù títí dìgbà tí Ọlọ́run máa mú àwọn ìlérí ẹ̀ ṣẹ. (Héb. 6:​11, 12) Bíbélì fi àwa ìránṣẹ́ Jèhófà wé àgbẹ̀ kan. (Jém. 5:​7, 8) Àwọn àgbẹ̀ máa ń ṣiṣẹ́ kára láti gbin nǹkan, kí wọ́n sì bomi rin ín, àmọ́ wọn ò mọ ìgbà tí nǹkan náà máa dàgbà. Ṣe ni wọ́n máa ń ní sùúrù, ó sì dá wọn lójú pé àwọn máa kórè lọ́jọ́ kan. Bọ́rọ̀ tiwa náà ṣe rí nìyẹn. Ó yẹ ká tẹra mọ́ ìjọsìn Ọlọ́run bó tiẹ̀ jẹ́ pé a “ò mọ ọjọ́ tí Olúwa [wa] ń bọ̀.” (Mát. 24:42) Torí náà, ó yẹ ká ní sùúrù kó sì dá wa lójú pé tó bá tó àkókò, Jèhófà máa mú gbogbo ìlérí ẹ̀ ṣẹ. Tá a bá dẹni tí ò ní sùúrù mọ́ torí pé ohun tá à ń dúró dè ò tètè dé, ó lè sú wa, ó sì lè jẹ́ ká fi Jèhófà sílẹ̀. A tún lè bẹ̀rẹ̀ sí í lé àwọn nǹkan tá a rò pé ó lè mára tù wá lójú ẹsẹ̀. Àmọ́ tá a bá ní sùúrù, á jẹ́ ká lè fara dà á dé òpin, àá sì rí ìgbàlà.—Míkà 7:7. w23.08 22 ¶7

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Tuesday, June 10

Ọmọ ìka ẹsẹ̀ náà jẹ́ apá kan irin àti apá kan amọ̀.—Dán. 2:42.

Tá a bá fi àsọtẹ́lẹ̀ inú Dáníẹ́lì 2:​41-43 wé àwọn àsọtẹ́lẹ̀ míì nínú ìwé Dáníẹ́lì àti Ìfihàn, a máa rí i pé ẹsẹ̀ ère yẹn ṣàpẹẹrẹ ìjọba alágbára tó ń ṣàkóso ayé báyìí, ìyẹn ìjọba Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà. Dáníẹ́lì sọ pé ìjọba yẹn “máa lágbára lápá kan,” “kò sì ní lágbára lápá kan.” Kí nìdí tí ò fi ní lágbára lápá kan? Ìdí ni pé àwọn mẹ̀kúnnù tó ṣàpẹẹrẹ amọ̀ rírọ̀ ò jẹ́ kí ìjọba Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà tó ń ṣàkóso wọn lo agbára ẹ̀ tó dà bí irin bó ṣe fẹ́. Àlàyé tí Dáníẹ́lì ṣe nípa ère inú àlá yẹn jẹ́ ká mọ àwọn òótọ́ pọ́ńbélé kan. Àkọ́kọ́, ìjọba Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà ti ṣe àwọn nǹkan tó fi hàn pé òun lágbára. Bí àpẹẹrẹ, àwọn orílẹ̀-èdè méjì yìí ló gbawájú lára àwọn orílẹ̀-èdè tó ṣẹ́gun nígbà Ogun Àgbáyé Kìíní àti Ogun Àgbáyé Kejì. Àmọ́, ìjọba alágbára yìí ò lágbára bíi ti tẹ́lẹ̀ mọ́ torí pé àwọn ará ìlú máa ń bá ara wọn àti ìjọba jà. Ìkejì, ìjọba alágbára yìí ló máa ṣàkóso ayé kẹ́yìn kí Ìjọba Ọlọ́run tó fòpin sí gbogbo ìjọba èèyàn. w23.08 11 ¶12-13

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Wednesday, June 11

Mo ké pe Jèhófà nínú wàhálà mi, mo sì ń kígbe sí Ọlọ́run mi fún ìrànlọ́wọ́. Ó gbọ́ ohùn mi láti tẹ́ńpìlì rẹ̀.—Sm. 18:6.

Nígbà míì, nǹkan máa ń tojú sú Dáfídì nítorí àwọn ìṣòro tó ní àti àdánwò tó dé bá a. (Sm. 18:​4, 5) Síbẹ̀, ìfẹ́ oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ tí Jèhófà fi hàn sí i àti bó ṣe bójú tó o tù ú lára. Jèhófà darí ọ̀rẹ́ ẹ̀ tó ti rẹ̀ lọ sí “ibi ìjẹko tútù” àti “ibi ìsinmi tó lómi dáadáa.” Àwọn nǹkan tí Jèhófà ṣe yìí ló fún Dáfídì lókun, tó sì jẹ́ kó máa fayọ̀ sìn ín nìṣó. (Sm. 18:​28-32; 23:2) Bákan náà lónìí, “ìfẹ́ Jèhófà tí kì í yẹ̀ ni ò jẹ́ ká ṣègbé” láwọn ìgbà tá a níṣòro. (Ìdárò 3:22; Kól. 1:11) Ọ̀pọ̀ ìgbà ni ẹ̀mí Dáfídì wà nínú ewu, ó láwọn ọ̀tá tó lágbára, wọ́n sì pọ̀. Síbẹ̀ torí pé ó mọ̀ pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ òun, ọkàn ẹ̀ balẹ̀, Jèhófà sì dáàbò bò ó. Dáfídì mọ̀ pé gbogbo ìgbà ni Jèhófà wà pẹ̀lú òun, ìyẹn sì máa ń jẹ́ kọ́kàn ẹ̀ balẹ̀ nígbà ìṣòro. Ìdí nìyẹn tó fi kọrin pé: “[Jèhófà] gbà mí sílẹ̀ nínú gbogbo ohun tó ń bà mí lẹ́rù.” (Sm. 34:4) Òótọ́ ni pé àwọn ìgbà kan wà tí ẹ̀rù ba Dáfídì, àmọ́ ìfẹ́ tí Jèhófà ní sí i mú kó borí ìbẹ̀rù náà. w24.01 30 ¶15-17

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́