ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2026)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Friday, December 26

Alábàáṣiṣẹ́ pẹ̀lú Ọlọ́run ni wá.—1 Kọ́r. 3:9.

Òtítọ́ lọ̀rọ̀ inú Bíbélì, ó sì lágbára gan-an. Bá a ṣe ń kọ́ àwọn èèyàn nípa Jèhófà àti irú ẹni tó jẹ́, ohun tí wọ́n mọ̀ nípa ẹ̀ ń yà wọ́n lẹ́nu. Ohun tí wọ́n ń kọ́ yẹn jẹ́ kí wọ́n rí i pé irọ́ ni Sátánì ń pa, wọ́n wá mọ̀ pé Jèhófà láwọn ànímọ́ tó dáa. Ẹnu yà wọ́n gan-an nítorí agbára ẹ̀ tí ò láàlà. (Àìsá. 40:26) Ohun tí wọ́n kọ́ jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í gbẹ́kẹ̀ lé e torí wọ́n rí i pé onídàájọ́ òdodo ni. (Diu. 32:4) Wọ́n tún kẹ́kọ̀ọ́ pé òun ló gbọ́n jù. (Àìsá. 55:9; Róòmù 11:33) Ara tù wọ́n nígbà tí wọ́n mọ̀ pé Ọlọ́run jẹ́ ìfẹ́. (1 Jòh. 4:8) Bí wọ́n ṣe ń mọ Jèhófà sí i, bẹ́ẹ̀ ló ń dá wọn lójú pé àwọn máa wà láàyè títí láé. Ẹ ò rí i pé àǹfààní ńlá la ní láti ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ kí wọ́n lè sún mọ́ Bàbá wa ọ̀run! Tá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, Jèhófà máa pè wá ní “alábàáṣiṣẹ́” òun.—1 Kọ́r. 3:5. w24.02 12 ¶15

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Saturday, December 27

Ó sàn kí o má ṣe jẹ́jẹ̀ẹ́ ju pé kí o jẹ́jẹ̀ẹ́, kí o má sì san án.—Oníw. 5:5.

Tó bá jẹ́ pé o ṣì ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì pẹ̀lú àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà tàbí táwọn òbí ẹ jẹ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà, ṣé ó ń wù ẹ́ pé kó o ṣèrìbọmi? Tó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, ohun tó dáa lo fẹ́ ṣe yẹn! Àmọ́ kó o tó lè ṣèrìbọmi, o gbọ́dọ̀ kọ́kọ́ ya ara ẹ sí mímọ́ fún Jèhófà. Báwo lo ṣe máa ya ara ẹ sí mímọ́ fún Jèhófà? O máa ṣèlérí fún un nínú àdúrà pé òun nìkan ni wàá máa sìn àti pé bó o ṣe máa ṣe ìfẹ́ ẹ̀ lá ṣe pàtàkì jù sí ẹ. Ńṣe lo máa ṣèlérí fún un pé wàá nífẹ̀ẹ́ ẹ̀ pẹ̀lú “gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo ara rẹ àti gbogbo èrò rẹ àti gbogbo okun rẹ.” (Máàkù 12:30) Tó o bá fẹ́ ya ara ẹ sí mímọ́, kò sẹ́nì kankan tó máa mọ̀ torí àárín ìwọ àti Jèhófà nìkan lọ̀rọ̀ náà wà. Àmọ́ ojú ọ̀pọ̀ èèyàn lo ti máa ṣèrìbọmi, ìyẹn sì máa jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé o ti ya ara ẹ sí mímọ́. Ẹ̀jẹ́ tó o jẹ́ nígbà tó o ya ara ẹ sí mímọ́ ṣe pàtàkì gan-an, torí náà Jèhófà fẹ́ kó o mú ẹ̀jẹ́ yẹn ṣẹ, ó sì dájú pé ohun tíwọ fúnra ẹ náà fẹ́ ṣe nìyẹn.—Oníw. 5:4. w24.03 2 ¶2; 3 ¶5

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Sunday, December 28

Kálukú yín gbọ́dọ̀ nífẹ̀ẹ́ aya rẹ̀ bó ṣe nífẹ̀ẹ́ ara rẹ̀; bákan náà, kí aya ní ọ̀wọ̀ tó jinlẹ̀ fún ọkọ rẹ̀.—Éfé. 5:33.

Kò sí ìgbéyàwó tí ò níṣòro tiẹ̀. Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé bó ṣe rí nìyẹn nígbà tó sọ pé àwọn tó ṣègbéyàwó máa ní “ìpọ́njú nínú ara wọn.” (1 Kọ́r. 7:28) Kí nìdí? Ìdí ni pé aláìpé làwọn méjèèjì, ìwà wọn yàtọ̀ síra, ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ sì lohun tí kálukú wọn nífẹ̀ẹ́ sí. Yàtọ̀ síyẹn, ibi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni wọ́n ti wá, àṣà wọn sì yàtọ̀ síra. Tó bá yá, wọ́n lè bẹ̀rẹ̀ sí í rí àwọn ìwà tí wọn ò mọ̀ pé ọkọ tàbí aya wọn ní kí wọ́n tó ṣègbéyàwó. Tí wọn ò bá sì ṣọ́ra, ìyẹn lè fa ìṣòro. Dípò kí wọ́n máa di ẹ̀bi ohun tó ṣẹlẹ̀ náà ru ọkọ tàbí aya wọn, ńṣe ló yẹ kí ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn gbà pé òun jẹ̀bi lọ́nà kan, kí wọ́n sì wá bí wọ́n ṣe máa yanjú ìṣòro náà. Wọ́n tiẹ̀ lè máa wò ó pé ohun tó máa yanjú ìṣòro náà ni pé káwọn pínyà tàbí kọ ara wọn sílẹ̀. Àmọ́ ṣéyẹn máa yanjú ìṣòro náà? Rárá o. Jèhófà ò fẹ́ kí tọkọtaya kọ ara wọn sílẹ̀ kódà tí ìwà ọkọ tàbí aya yẹn bá burú. w24.03 16 ¶8; 17 ¶11

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́