Thursday, February 12
Nígbà tí àníyàn bò mí mọ́lẹ̀, o tù mí nínú, o sì tù mí lára.—Sm. 94:19.
Kí lo lè ṣe tó o bá ń rò pé o ò já mọ́ nǹkan kan? Máa ka àwọn ẹsẹ Bíbélì tó máa jẹ́ kó dá ẹ lójú pé o ṣeyebíye lójú Jèhófà, kó o sì máa ṣàṣàrò nípa wọn. Tọ́wọ́ ẹ ò bá tẹ ohun tó ò ń lé tàbí tó ò lè ṣe tó àwọn ẹlòmíì, má ṣe dá ara ẹ lẹ́bi. Jèhófà ò fẹ́ kó o ṣe ohun tágbára ẹ ò gbé. (Sm. 103:13, 14) Tẹ́nì kan bá hùwà ìkà sí ẹ, ìwọ kọ́ lo jẹ̀bi torí kò yẹ kó hùwà yẹn sí ẹ. Rántí pé Jèhófà máa fìyà jẹ ẹni náà, ó sì máa tù ẹ́ nínú. (1 Pét. 3:12) Má rò pé Jèhófà ò lè lò ẹ́ láti ran àwọn èèyàn lọ́wọ́. Àǹfààní ńlá ni pé ò ń bá Jèhófà ṣiṣẹ́ bó o ṣe ń wàásù fáwọn èèyàn. (1 Kọ́r. 3:9) Àwọn nǹkan tó ti ṣẹlẹ̀ sí ẹ rí lè mú kó o mọ bọ́rọ̀ ṣe rí lára àwọn tó ń jìyà, ìyẹn á sì mú kó o káàánú wọn. Ọ̀pọ̀ nǹkan lo sì lè ṣe láti ràn wọ́n lọ́wọ́. w24.10 7-8 ¶6-7
Friday, February 13
Ṣé kò wá dájú pé Ọlọ́run máa mú kí a dájọ́ bó ṣe tọ́ fún àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ tí wọ́n ń ké pè é tọ̀sántòru, bó ṣe ń ní sùúrù fún wọn? Mò ń sọ fún yín, ó máa mú kí a dá ẹjọ́ wọn bó ṣe tọ́ kíákíá.—Lúùkù 18:7, 8.
Jèhófà kì í fẹ́ kí nǹkan burúkú ṣẹlẹ̀ sí wa, ó sì máa ń kíyè sí i táwọn èèyàn bá hùwà tí ò dáa sí wa. Bíbélì sọ pé “Jèhófà nífẹ̀ẹ́ ìdájọ́ òdodo.” (Sm. 37:28) Jésù fi dá wa lójú pé Jèhófà “máa mú kí a dá ẹjọ́ bó ṣe tọ́ kíákíá” tó bá tó àkókò lójú ẹ̀. Bákan náà láìpẹ́, Jèhófà máa mú gbogbo ìwà ìrẹ́jẹ àtohun tó ti fà kúrò pátápátá. (Sm. 72:1, 2) Bá a ṣe ń dúró de ìgbà tí gbogbo èèyàn á máa hùwà tó dáa, Jèhófà máa ràn wá lọ́wọ́ láti fara da ìwà ìrẹ́jẹ táwọn èèyàn ń hù sí wa. (2 Pét. 3:13) Ó máa ń kọ́ wa ní ohun tá a máa ṣe táwọn èèyàn bá hùwà tí ò dáa sí wa ká má bàa ṣìwà hù. Bó ṣe ṣe é ni pé ó jẹ́ kí wọ́n ṣàkọsílẹ̀ ohun tí Jésù Ọmọ ẹ̀ ṣe nígbà tí wọ́n hùwà tí ò dáa sí i, ká lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ẹ̀. Ó sì tún fún wa láwọn ìmọ̀ràn tá a lè tẹ̀ lé táwọn èèyàn bá hùwà tí ò dáa sí wa. w24.11 2-3 ¶3-4
Saturday, February 14
Ẹ fún wọn ní nǹkan tí wọ́n máa jẹ.—Mát. 14:16.
Jésù sọ fáwọn àpọ́sítélì ẹ̀ pé kí wọ́n fún èrò rẹpẹtẹ tó wà lọ́dọ̀ wọn ní nǹkan tí wọ́n máa jẹ. Àmọ́ ìṣòro ńlá nìyẹn o torí nǹkan bí ẹgbẹ̀rún márùn-ún (5,000) ọkùnrin ló wà níbẹ̀. Tá a bá wá fi àwọn obìnrin àtàwọn ọmọdé tó wà níbẹ̀ kún un, wọ́n á tó nǹkan bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún (15,000) tí wọ́n máa fún lóúnjẹ. (Mát. 14:21) Áńdérù wá sọ pé: “Ọmọdékùnrin kan nìyí tó ní búrẹ́dì ọkà báálì márùn-ún àti ẹja kéékèèké méjì. Àmọ́ kí ni èyí já mọ́ láàárín àwọn tó pọ̀ tó yìí?” (Jòh. 6:9) Láyé ìgbà yẹn, ọ̀pọ̀ èèyàn títí kan àwọn tálákà ló sábà máa ń jẹ búrẹ́dì tí wọ́n fi ọkà báálì ṣe, ó sì ṣeé ṣe kí wọ́n ti fi iyọ̀ sí ẹja kéékèèké náà, kí wọ́n sì ti yan án gbẹ. Síbẹ̀, ẹja tí ọmọ náà ní ò lè tó láti bọ́ gbogbo èèyàn yẹn. Àbí ẹ rò pé ó lè tó? Torí pé Jésù fẹ́ kí ara tu àwọn èèyàn náà, ó ní kí wọ́n jókòó ní àwùjọ àwùjọ sórí koríko. (Máàkù 6:39, 40; Jòh. 6:11-13) Ẹsẹ Bíbélì yẹn sọ pé Jésù dúpẹ́ lọ́wọ́ Bàbá ẹ̀ torí búrẹ́dì àti ẹja náà. Ó sì ṣe pàtàkì kó dúpẹ́ torí pé Jèhófà ló pèsè oúnjẹ náà. Bíi ti Jésù, ó yẹ káwa náà máa gbàdúrà ká tó jẹun. Lẹ́yìn ìyẹn, Jésù ní káwọn ọmọlẹ́yìn òun pín oúnjẹ náà fáwọn èèyàn. Àwọn èèyàn jẹun, wọ́n sì yó bámú. w24.12 2-3 ¶3-4