Sunday, September 8
Kí o sì yan ìyè, kí o lè máa wà láàyè nìṣó, ìwọ àti ọmọ rẹ.—Diu. 30:19.
Tó o bá fẹ́ káwọn ọmọ rẹ nígbàgbọ́, ó kọjá kó o kàn máa sọ fún wọn pé ohun kan ló tọ́ tàbí pé ohun kan ni kò tọ́. Á dáa kó o tún mọ èrò wọn. O ò ṣe bi wọ́n láwọn ìbéèrè bíi: ‘Kí nìdí tí Bíbélì fi sọ pé kó o sá fún àwọn nǹkan tí ẹran ara ń fẹ́? Kí ló jẹ́ kó dá ẹ lójú pé ìgbà gbogbo làwọn ìlànà Bíbélì máa ń ṣeni láǹfààní?’ (Aísá. 48:17, 18) Ohun míì wà tó tún yẹ kó o jíròrò pẹ̀lú ọmọ rẹ tó fẹ́ ṣèrìbọmi. Ṣó mọ ohun tó túmọ̀ sí pé kéèyàn ṣèrìbọmi àti ojúṣe tó wé mọ́ jíjẹ́ Kristẹni? Àǹfààní wo ló máa rí tó bá ṣèrìbọmi? Àwọn ìṣòro wo ló lè jẹ yọ? Báwo làwọn àǹfààní ibẹ̀ ṣe ju àwọn ìṣòro tó ṣeé ṣe kó yọjú lọ? (Máàkù 10:29, 30) Ó ṣeé ṣe kó dojú kọ àwọn ipò tó máa dán ìgbàgbọ́ rẹ̀ wò lẹ́yìn tó bá ṣèrìbọmi. Torí náà, ó ṣe pàtàkì kọ́mọ rẹ ronú jinlẹ̀ nípa àwọn ìbéèrè yìí dáadáa kó tó ṣèrìbọmi. Tẹ́ ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, á túbọ̀ rọrùn fún wọn láti ṣèpinnu tó mọ́gbọ́n dání, wọ́n á sì ní ìdánilójú pé ìgbà gbogbo làwọn ìlànà Bíbélì máa ń ṣeni láǹfààní. w17.12 21-22 ¶14-15
Monday, September 9
Àní orúkọ ni ó fi ń pe gbogbo wọn.—Aísá. 40:26.
Ọ̀pọ̀ lára ẹ̀yin ará wa lọ́kùnrin àti lóbìnrin ló ń fara da àìsàn tó le. Ara ti ń dara àgbà fáwọn kan, síbẹ̀ wọ́n tún láwọn arúgbó tí wọ́n ń tọ́jú. Ṣe làwọn kan ń tiraka kí wọ́n lè rọ́wọ́ mú lọ sẹ́nu, bí wọ́n ṣe máa gbọ́ bùkátà ìdílé wọn ni wọ́n ń wá, kì í ṣe bí wọ́n ṣe máa ní ànító àti àníṣẹ́kù. Bá a ṣe mọ̀, ńṣe làwọn ìṣòro yìí ń rọ́ lura fáwọn kan lára wa, ó mà ṣe o! Tí Jèhófà bá ń kíyè sí àwọn nǹkan tí kò lẹ́mìí, mélòómélòó wá ni ìwọ tó ò ń fi tọkàntọkàn sìn ín torí pé o nífẹ̀ẹ́ rẹ̀. (Sm. 19:1, 3, 14) Baba wa ọ̀run mọ̀ ẹ́ dáadáa. Kódà, ‘gbogbo irun orí rẹ ni Jèhófà ti kà.’ (Mát. 10:30) Onísáàmù náà tún jẹ́ kó dá wa lójú pé Jèhófà mọ ohun táwọn aláìní-àléébù ń kojú. (Sm. 37:18) Ó mọ gbogbo ìṣòro tó ò ń dojú kọ, ó sì máa fún ẹ lókun láti fara dà á. w18.01 7 ¶1; 8 ¶4
Tuesday, September 10
Tàbítà, dìde!—Ìṣe 9:40.
Àpọ́sítélì Pétérù jí Tàbítà dìde, ó sì ya àwọn tó wà níbẹ̀ lẹ́nu gan-an débi pé ‘ọ̀pọ̀ ènìyàn di onígbàgbọ́ nínú Olúwa.’ Ó dájú pé àwọn ọmọ ẹ̀yìn yìí á jẹ́rìí nípa Jésù, wọ́n á sì sọ fáwọn míì pé Jèhófà lè jí òkú dìde. (Ìṣe 9:36-42) Àjíǹde míì tún wáyé níṣojú àwọn èèyàn. Ìgbà kan wà tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ń ṣèpàdé pẹ̀lú àwọn ará nínú yàrá òkè kan nílùú Tíróásì, tó jẹ́ apá kan orílẹ̀-èdè Tọ́kì báyìí. Pọ́ọ̀lù bá wọn sọ̀rọ̀ títí di òru. Ọmọkùnrin kan tó ń jẹ́ Yútíkọ́sì jókòó sẹ́gbẹ̀ẹ́ wíńdò, ó ń gbọ́ ohun tí Pọ́ọ̀lù ń sọ. Àmọ́ ó bẹ̀rẹ̀ sí í tòògbé, ló bá ré bọ́ látorí àjà kẹta ilé náà. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé Lúùkù oníṣègùn ló kọ́kọ́ dé ọ̀dọ̀ Yútíkọ́sì kó lè mọ ohun tó ṣẹlẹ̀ sí i. Lẹ́yìn tí Lúùkù sì ti yẹ̀ ẹ́ wò, ó rí i pé kì í ṣe pé Yútíkọ́sì ṣèṣe tàbí pé ó dákú, ṣe ló kú fin-ín-fin-ín, ìyẹn sì ba àwọn ará nínú jẹ́ gan-an. Pọ́ọ̀lù sọ̀ kalẹ̀, ó gbé òkú náà mọ́ra, ó wá sọ pé: Ó ti jíǹde o! Ẹ ò rí i pé ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn máa wú àwọn tó wà níbẹ̀ lórí gan-an! Bí wọ́n ṣe mọ̀ pé ọmọkùnrin náà ti kú tẹ́lẹ̀ tí Pọ́ọ̀lù sì jí i dìde mú kí wọ́n ní ìtùnú “lọ́nà tí kò ṣeé díwọ̀n.”—Ìṣe 20:7-12. w17.12 5 ¶10-11