Sunday, April 26
Bí Jèhófà ṣe dárí jì yín ní fàlàlà, ẹ̀yin náà gbọ́dọ̀ máa ṣe bẹ́ẹ̀.—Kól. 3:13.
Jèhófà fẹ́ ká dárí ji àwọn èèyàn nígbàkigbà tí wọ́n bá ṣe ohun tó dùn wá. (Sm. 86:5; Lúùkù 17:4; Éfé. 4:32) Ó lè dùn wá gan-an tẹ́nì kan bá ṣe ohun tí ò dáa sí wa, pàápàá tẹ́ni náà bá jẹ́ ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ tàbí ará ilé wa. (Sm. 55:12-14) Nígbà míì, ẹ̀dùn ọkàn tá a máa ń ní máa ń dà bí ìgbà tí wọ́n fi idà gún wa. (Òwe 12:18) A lè fẹ́ pa á mọ́ra tàbí ká má ṣe nǹkan kan sí i. Àmọ́ tá a bá ṣe bẹ́ẹ̀, ńṣe ló dà bí ìgbà tẹ́nì kan gún wa lọ́bẹ, tí kò sì yọ ọ́ kúrò níbẹ̀. Lọ́nà kan náà, a ò lè retí pé kí ẹ̀dùn ọkàn wa lọ tá ò bá wá nǹkan ṣe sí i. Tẹ́nì kan bá ṣe ohun tó dùn wá, a lè kọ́kọ́ fẹ́ fara ya. Bíbélì tiẹ̀ sọ pé inú lè bí wa. Àmọ́ Bíbélì kìlọ̀ fún wa pé ká má jẹ́ kí ìbínú yẹn mú ká dẹ́ṣẹ̀. (Sm. 4:4; Éfé. 4:26) Kí nìdí? Ìdí ni pé tẹ́nì kan bá tètè ń bínú, ohun tí ò dáa lá máa ṣe. (Jém. 1:20) Ẹ má gbàgbé pé tẹ́nì kan bá ṣẹ̀ wá, a lè fi bí nǹkan ṣe rí lára wa hàn, àmọ́ kò yẹ ká fàáké kọ́rí, ká wá máa bínú sẹ́ni náà títí lọ. w25.02 15 ¶4-6
Monday, April 27
Ọgbọ́n máa ń dá ẹ̀mí àwọn tó ní in sí.—Oníw. 7:12.
Jésù jẹ́ ká mọ̀ nínú àpèjúwe kan tó ṣe pé ìwà òmùgọ̀ ni kéèyàn kówó jọ pelemọ, kó má sì ní “ọrọ̀ lọ́dọ̀ Ọlọ́run.” (Lúùkù 12:16-21) Ká sòótọ́, a ò mohun tó lè ṣẹlẹ̀ sí wa lọ́la. (Òwe 23:4, 5; Jém. 4:13-15) Jésù sọ pé gbogbo àwọn tó bá fẹ́ di ọmọlẹ́yìn òun gbọ́dọ̀ “yááfì” àwọn ohun ìní wọn, ìyẹn ò sì rọrùn. (Lúùkù 14:33, àlàyé ìsàlẹ̀) Ohun táwọn Kristẹni àkọ́bẹ̀rẹ̀ tó ń gbé Jùdíà ṣe nìyẹn. (Héb. 10:34) Lákòókò wa yìí, ọ̀pọ̀ àwọn ará wa ló ti pàdánù iṣẹ́ tàbí ohun ìní wọn torí pé wọn ò ti ẹgbẹ́ òṣèlú lẹ́yìn. (Ìfi. 13:16, 17) Kí ló jẹ́ kí wọ́n ṣe bẹ́ẹ̀? Wọ́n gbà pé Jèhófà máa mú ìlérí ẹ̀ ṣẹ nígbà tó sọ pé: “Mi ò ní fi ọ́ sílẹ̀ láé, mi ò sì ní pa ọ́ tì láé.” (Héb. 13:5) Síbẹ̀, àá sapá láti múra sílẹ̀ de ọjọ́ iwájú, àmọ́ tóhun tá ò retí bá ṣẹlẹ̀, àá gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà pé ó máa bójú tó wa. w25.03 29 ¶13-14
Tuesday, April 28
Ní báyìí tí a ti kọjá àwọn ẹ̀kọ́ àkọ́bẹ̀rẹ̀ nípa Kristi, ẹ jẹ́ ká tẹ̀ síwájú, ká dàgbà nípa tẹ̀mí, ká má ṣe tún máa fi ìpìlẹ̀ lélẹ̀ mọ́.—Héb. 6:1.
Tá a bá fẹ́ di Kristẹni tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú ẹ̀, agbára wa nìkan ò gbé e, àfi ká jẹ́ kí Jèhófà ràn wá lọ́wọ́. Ó máa ń lo àwọn alábòójútó tí wọ́n tún jẹ́ olùkọ́ nínú ìjọ Kristẹni láti ràn wá lọ́wọ́ ká lè “di géńdé” tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú ẹ̀, ká sì “dàgbà dé ìwọ̀n kíkún ti Kristi.” (Éfé. 4:11-13) Jèhófà tún máa ń fi ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ ká lè ní “èrò inú Kristi.” (1 Kọ́r. 2:14-16) Yàtọ̀ síyẹn, Ọlọ́run tún jẹ́ kí wọ́n kọ àwọn Ìwé Ìhìn Rere mẹ́rin tó jẹ́ ká mọ bí Jésù ṣe ronú, bó ṣe sọ̀rọ̀ àti bó ṣe hùwà nígbà tó wà láyé. Tó o bá ń ronú bíi ti Jésù, tó o sì ń hùwà bíi tiẹ̀, wàá di Kristẹni tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú ẹ̀. Àmọ́, ká tó lè di Kristẹni tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú ẹ̀, ohun tá a mọ̀ gbọ́dọ̀ “kọjá àwọn ẹ̀kọ́ àkọ́bẹ̀rẹ̀ nípa Kristi,” ìyẹn àwọn ohun tá a kọ́kọ́ mọ̀ nígbà tá a di Kristẹni. w24.04 4-5 ¶11-12