Wednesday, April 22
Kristi pàápàá jìyà torí yín, ó fi àpẹẹrẹ lélẹ̀ fún yín kí ẹ lè máa tọ ipasẹ̀ rẹ̀ pẹ́kípẹ́kí.—1 Pét. 2:21.
Jésù fi àpẹẹrẹ lélẹ̀ ká lè mọ bá a ṣe máa fara dà á tí wọ́n bá hùwà tí ò dáa sí wa. Ẹ jẹ́ ká wo díẹ̀ lára ìwà burúkú táwọn ìdílé ẹ̀ àtàwọn míì hù sí i. Torí pé àwọn mọ̀lẹ́bí ẹ̀ ò gbà á gbọ́, wọ́n sọ pé orí ẹ̀ ti yí, àwọn aṣáájú ẹ̀sìn sì fẹ̀sùn kàn án pé ẹ̀mí èṣù ló fi ń ṣiṣẹ́ ìyanu. Yàtọ̀ síyẹn, àwọn ọmọ ogun Róòmù bú u, wọ́n lù ú nílùkulù, nígbẹ̀yìn-gbẹ́yín, wọ́n pa á. (Máàkù 3:21, 22; 14:55; 15:16-20, 35-37) Síbẹ̀, Jésù fara da gbogbo ìwà burúkú tí wọ́n hù sí i, kò sì gbẹ̀san. Kí la kọ́ látinú àpẹẹrẹ ẹ̀? (1 Pét. 2:21-23) Jésù fi àpẹẹrẹ lélẹ̀ fún wa ká lè mọ ohun tá a máa ṣe tí wọ́n bá hùwà tí ò dáa sí wa. Ó mọ̀gbà tó yẹ kóun dákẹ́ àtìgbà tó yẹ kóun sọ̀rọ̀. (Mát. 26:62-64) Kì í ṣe gbogbo ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn án ló fèsì. (Mát. 11:19) Tó bá sì sọ̀rọ̀, kì í bú àwọn alátakò ẹ̀ tàbí kó halẹ̀ mọ́ wọn. w24.11 4-5 ¶9-10
Thursday, April 23
Kristi Jésù wá sí ayé láti gba àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ là.—1 Tím. 1:15.
Fojú inú wò ó pé o fún ẹni tó o fẹ́ràn lẹ́bùn kan tó rẹwà, tó sì máa wúlò fún un. Ó máa dùn ẹ́ gan-an tó o bá rí i pé ẹni náà ju ẹ̀bùn náà síbì kan, tí ò sì lò ó! Àmọ́, ó dájú pé inú ẹ máa dùn tẹ́ni náà bá lo ẹ̀bùn náà dáadáa, tó sì tún dúpẹ́ lọ́wọ́ ẹ. Kí nìyẹn kọ́ wa? Jèhófà jẹ́ kí Ọmọ ẹ̀ kú nítorí wa. Ẹ ò rí i pé inú Jèhófà máa dùn gan-an tó bá rí i pé a mọyì ìràpadà àti ìfẹ́ tó ní sí wa tó mú kó pèsè ìràpadà náà! (Jòh. 3:16; Róòmù 5:7, 8) Bọ́jọ́ ṣe ń gorí ọjọ́, a lè bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe ohun tó fi hàn pé a ò mọyì ìràpadà mọ́. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé inú wa dùn pé Ọlọ́run fún wa lẹ́bùn náà, ńṣe ló dà bí ìgbà tá a kàn ju ẹ̀bùn náà síbì kan. Tá ò bá fẹ́ kíyẹn ṣẹlẹ̀ sí wa, gbogbo ìgbà ló yẹ ká máa ronú nípa ohun tí Ọlọ́run àti Kristi ṣe fún wa. w25.01 26 ¶1-2
Friday, April 24
Máa ronú lórí àwọn nǹkan yìí; jẹ́ kó gbà ọ́ lọ́kàn, kí gbogbo èèyàn lè rí i kedere pé ò ń tẹ̀ síwájú.—1 Tím. 4:15.
Arákùnrin tó fẹ́ di alàgbà ò ní jẹ́ ẹni tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ yí lọ́kàn pa dà. Kò pọn dandan kó o ti ṣèrìbọmi tipẹ́ kó o tó lè di alàgbà, àmọ́ ó máa gba pé kí òtítọ́ kọ́kọ́ jinlẹ̀ nínú ẹ, ìyẹn sì máa gba àkókò. Kó o tó lè di alàgbà, o gbọ́dọ̀ fara wé Jésù, kó o nírẹ̀lẹ̀, kó o sì máa fi sùúrù dúró de iṣẹ́ ìsìn èyíkéyìí tí Jèhófà máa yàn fún ẹ. (Mát. 20:23; Fílí. 2:5-8) O máa fi hàn pé “olóòótọ́” ni ẹ́ tó o bá ń tẹ̀ lé ìlànà òdodo Jèhófà, tó o sì ń ṣe ohun tí ètò Ọlọ́run bá sọ. Bíbélì sọ pé àwọn alábòójútó gbọ́dọ̀ kúnjú ìwọ̀n láti kọ́ni. Ṣóhun tó ń sọ ni pé ẹni náà gbọ́dọ̀ jẹ́ sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀? Rárá. Kì í ṣe gbogbo alàgbà ló jẹ́ sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ tó dáńtọ́, àmọ́ gbogbo wọn máa ń kọ́ni dáadáa tí wọ́n bá ń wàásù àti nígbà tí wọ́n bá ń fún àwọn ará níṣìírí nígbà ìbẹ̀wò olùṣọ́ àgùntàn. w24.11 23-24 ¶14-15