Wednesday, August 12
Ipasẹ̀ ìràpadà tó fi ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ san ni a fi rí ìtúsílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni, ìdáríjì àwọn àṣemáṣe wa, nítorí ọlá inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí rẹ̀.—Éfé. 1:7.
Bí Jésù ṣe jẹ́ ẹni pípé náà ni Ádámù jẹ́ ẹni pípé kó tó dẹ́ṣẹ̀. (1 Kọ́r. 15:45) Bí Jésù ṣe kú jẹ́ kó lè mú ẹ̀ṣẹ̀ Ádámù kúrò, kó sì san ohun tó pàdánù. (Róòmù 5:19) Bí Jésù ṣe di “Ádámù ìkẹyìn” nìyẹn. A ò sì nílò ẹlòmíì tó jẹ́ ẹni pípé láti wá san ohun tí Ádámù pàdánù torí pé Jésù ti kú “lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo láìtún ní ṣe é mọ́ láé.” (Héb. 7:27; 10:12) Ìyàtọ̀ wo ló wà láàárín ètùtù àti ìràpadà? Ètùtù ni ohun tí Ọlọ́run ṣe láti jẹ́ kí àjọṣe òun àti aráyé pa dà gún régé. Ìràpadà ni ohun tí Ọlọ́run san láti fi ṣètùtù fún aráyé nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa. Ẹ̀jẹ̀ iyebíye tí Jésù dà jáde nítorí wa ni ohun tí Ọlọ́run san.—Héb. 9:14. w25.02 5 ¶12-13
Thursday, August 13
Ọlọ́run jẹ́ olóòótọ́, kò ní jẹ́ kí a dán yín wò kọjá ohun tí ẹ lè mú mọ́ra, ṣùgbọ́n nínú àdánwò náà, yóò ṣe ọ̀nà àbáyọ kí ẹ lè fara dà á.—1 Kọ́r. 10:13.
Tá a bá gbà pé Ọlọ́run alààyè ni Jèhófà, àá máa fojú tó tọ́ wo ìṣòro wa. Báwo la ṣe lè ṣe é? A lè ṣe bẹ́ẹ̀ tá a bá rí i pé ìṣòro wa kan ọ̀rọ̀ tó ṣe pàtàkì jù, ìyẹn ọ̀tẹ̀ tí Sátánì dá sílẹ̀ nípa bóyá Jèhófà lẹ́tọ̀ọ́ láti ṣàkóso ayé àti ọ̀run. Èṣù sọ pé tọ́wọ́ ìyà bá bà wá, a máa fi Jèhófà sílẹ̀. (Jóòbù 1:10, 11; Òwe 27:11) Àmọ́ tá a bá jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà bó ti wù kí ìṣòro yẹn lágbára tó, á fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ Jèhófà àti pé òpùrọ́ ni Sátánì. Ṣé ìjọba ń ṣenúnibíni sí ẹ níbi tó ò ń gbé, ṣé àtijẹ àtimu nira fún ẹ, ṣé àwọn èèyàn kì í gbọ́ ìwàásù ní ìpínlẹ̀ ìwàásù yín àbí o láwọn ìṣòro míì tó ò ń bá yí? Tó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, má gbàgbé pé àwọn ìṣòro tó o ní yẹn ń fún ẹ láǹfààní láti múnú Jèhófà dùn. Tún máa rántí pé kò ní jẹ́ ká dán ẹ wò kọjá ohun tó o lè mú mọ́ra. Ó máa fún ẹ lókun kó o lè fara dà á. w24.06 22 ¶9
Friday, August 14
Àdánwò máa ń dé bá kálukú nígbà tí ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ bá fà á mọ́ra, tó sì tàn án jẹ.—Jém. 1:14.
Ṣé o mọ ìṣòro tìẹ, ìyẹn ohun tó máa ń dẹ ẹ́ wò? Ó léwu gan-an tá a bá ń rò pé a ò níṣòro kankan tàbí ká máa rò pé a ò lè dẹ́ṣẹ̀. (1 Jòh. 1:8) Ó ṣe tán, Pọ́ọ̀lù náà sọ pé àwọn tó “kúnjú ìwọ̀n nípa tẹ̀mí” náà lè dẹ́ṣẹ̀ tí wọn ò bá kíyè sára. (Gál. 6:1) Torí náà, ó yẹ kí kálukú bá ara ẹ̀ sọ òótọ́ ọ̀rọ̀, kó sì gbà pé òun níbi tóun kù sí. (2 Kọ́r. 13:5) Tá a bá ti mọ àwọn nǹkan tó máa ń dẹ wá wò, kí ló yẹ ká ṣe? Ṣe gbogbo nǹkan tó o lè ṣe kó o má bàa kó sínú ìdẹwò náà. Láyé ìgbà tí wọ́n ń kọ Bíbélì, ibi tó rọrùn jù fáwọn ọ̀tá láti gbà wọ ìlú olódi ni ẹnubodè rẹ̀. Ìdí nìyẹn tó fi jẹ́ pé àwọn ẹ̀ṣọ́ tó pọ̀ ló máa ń wà lẹ́nu ibodè. Lọ́nà kan náà, ó yẹ káwa náà máa kíyè sí ibi tá a kù sí lójú méjèèjì ká má bàa dẹ́ṣẹ̀.—1 Kọ́r. 9:27. w24.07 15 ¶5-7