ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Diutarónómì 24:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 “Tí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, àmọ́ tí obìnrin náà ò tẹ́ ẹ lọ́rùn torí ó rí ohun kan tí kò dáa nípa rẹ̀, kó kọ ìwé ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ fún un,+ kó fi lé e lọ́wọ́, kó sì ní kó kúrò ní ilé òun.+

  • Máàkù 10:2-12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 2 Àwọn Farisí wá sọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n fẹ́ dán an wò, wọ́n sì bi í bóyá ó bófin mu fún ọkùnrin láti kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀.+ 3 Ó dá wọn lóhùn pé: “Kí ni Mósè pa láṣẹ fún yín?” 4 Wọ́n sọ pé: “Mósè fàyè gba ká kọ ìwé ẹ̀rí láti lé e lọ, ká sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”+ 5 Àmọ́ Jésù sọ fún wọn pé: “Torí pé ọkàn yín le+ ló ṣe kọ àṣẹ yìí fún yín.+ 6 Ṣùgbọ́n ní ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀dá, ‘Ó dá wọn ní akọ àti abo.+ 7 Torí èyí, ọkùnrin á fi bàbá rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀,+ 8 àwọn méjèèjì á sì di ara kan,’+ tó fi jẹ́ pé wọn kì í ṣe méjì mọ́, àmọ́ wọ́n jẹ́ ara kan. 9 Torí náà, ohun tí Ọlọ́run ti so pọ̀, kí èèyàn kankan má ṣe yà á.”+ 10 Nígbà tí wọ́n tún wà nínú ilé, àwọn ọmọ ẹ̀yìn bẹ̀rẹ̀ sí í bi í nípa ọ̀rọ̀ yìí. 11 Ó sọ fún wọn pé: “Ẹnikẹ́ni tó bá kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀, tó sì fẹ́ ẹlòmíì ti ṣe àgbèrè,+ ó ti da obìnrin náà, 12 tí obìnrin kan bá sì lọ fẹ́ ọkùnrin míì, lẹ́yìn tó kọ ọkọ rẹ̀ sílẹ̀, ó ti ṣe àgbèrè.”+

Yorùbá Publications (1987-2026)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2026 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́