-
Mátíù 28:5-7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
5 Àmọ́ áńgẹ́lì náà sọ fún àwọn obìnrin náà pé: “Ẹ má bẹ̀rù, torí mo mọ̀ pé Jésù tí wọ́n kàn mọ́gi lẹ̀ ń wá.+ 6 Kò sí níbí, torí a ti jí i dìde, bó ṣe sọ gẹ́lẹ́.+ Ẹ wá wo ibi tí wọ́n tẹ́ ẹ sí. 7 Kí ẹ tètè lọ sọ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé a ti jí i dìde, torí ẹ wò ó! ó ń lọ sí Gálílì ṣáájú yín.+ Ẹ máa rí i níbẹ̀. Ẹ wò ó! Mo ti sọ fún yín.”+
-
-
Máàkù 16:5-7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
5 Nígbà tí wọ́n wọnú ibojì náà, wọ́n rí ọ̀dọ́kùnrin kan tó jókòó sẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀tún, ó wọ aṣọ funfun, ẹnu sì yà wọ́n. 6 Ó sọ fún wọn pé: “Ẹ má ṣe jẹ́ kó yà yín lẹ́nu.+ Jésù ará Násárẹ́tì tí wọ́n kàn mọ́gi lẹ̀ ń wá. A ti jí i dìde.+ Kò sí níbí. Ẹ wò ó, ibi tí wọ́n tẹ́ ẹ sí nìyí.+ 7 Àmọ́ ẹ lọ, ẹ sọ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ àti Pétérù pé, ‘Ó ń lọ sí Gálílì ṣáájú yín.+ Ẹ máa rí i níbẹ̀, bó ṣe sọ fún yín.’”+
-