14 Nígbà tí Jésù wọ ilé Pétérù, ó rí ìyá ìyàwó rẹ̀+ tí àìsàn ibà dá dùbúlẹ̀.+15 Ó sì fọwọ́ kan ọwọ́ obìnrin náà,+ ibà náà sì lọ, obìnrin náà wá dìde, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe ìránṣẹ́ fún un.
24 Jésù sọ pé: “Ẹ kúrò níbẹ̀, torí ọmọdébìnrin náà ò kú, ó ń sùn ni.”+ Ni wọ́n bá bẹ̀rẹ̀ sí í rẹ́rìn-ín, wọ́n sì ń fi ṣẹlẹ́yà. 25 Gbàrà tí wọ́n ní kí àwọn èrò náà bọ́ síta, ó wọlé, ó di ọwọ́ ọmọdébìnrin náà mú,+ ọmọ náà sì dìde.+