Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Gbólóhùn náà, ‘yóò sì fi òpin sí gbogbo ìjọba wọ̀nyí’ tó wà ní Dáníẹ́lì 2:44 ń tọ́ka sí àwọn ìjọba tí onírúurú apá tó wà nínú ère tí Dáníẹ́lì rí ṣàpẹẹrẹ. Ṣùgbọ́n, àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì mìíràn tó jọ èyí fi hàn pé “àwọn ọba gbogbo ilẹ̀ ayé tí a ń gbé pátá” máa kó ara wọn jọ lòdì sí Jèhófà ní “ọjọ́ ńlá Ọlọ́run Olódùmarè.” (Ìṣí. 16:14; 19:19-21) Torí náà, kì í ṣe àwọn ìjọba tí ère yẹn ṣàpẹẹrẹ nìkan ni ogun Amágẹ́dọ́nì máa pa run, ṣùgbọ́n ó tún máa pa gbogbo ìjọba yòókù nínú ayé run.