-
Àwámáridìí ni Títóbi JèhófàIlé Ìṣọ́—2004 | January 15
-
-
Àwọn Ànímọ́ Rere Tí Ọlọ́run Ní Mà Ga Lọ́lá O!
20, 21. (a) Ìwé Sáàmù 145:7-9 fi títóbi Jèhófà hàn nípa títọ́ka sí àwọn ànímọ́ wo? (b) Ipa wo ni àwọn ànímọ́ Ọlọ́run tá a mẹ́nu kàn níbí yìí ní lórí gbogbo àwọn tó nífẹ̀ẹ́ rẹ̀?
20 Gẹ́gẹ́ bá a ti kíyè sí i, àwọn ẹsẹ mẹ́fà àkọ́kọ́ nínú Sáàmù 145 fún wa ní ojúlówó ìdí tá a fi gbọ́dọ̀ máa yin Jèhófà fún àwọn nǹkan tó so pọ̀ mọ́ títóbi rẹ̀ tó jẹ́ àwámáridìí. Ẹsẹ keje sí ìkẹsàn-án fi títóbi Ọlọ́run hàn nípa títọ́ka sí àwọn ànímọ́ rere rẹ̀. Dáfídì kọrin pé: “Wọn yóò máa fi ọ̀yàyà sọ̀rọ̀ nígbà tí wọ́n bá ń mẹ́nu kan ọ̀pọ̀ yanturu oore rẹ, wọn yóò sì fi ìdùnnú ké jáde nítorí òdodo rẹ. Jèhófà jẹ́ olóore ọ̀fẹ́ àti aláàánú, Ó ń lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní inú-rere-onífẹ̀ẹ́. Jèhófà ń ṣe rere fún gbogbo gbòò, àánú rẹ̀ sì ń bẹ lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ̀.”
21 Oore àti òdodo Jèhófà ni Dáfídì kọ́kọ́ tẹnu mọ́ níhìn-ín—àwọn ànímọ́ wọ̀nyí sì ni Sátánì Èṣù sọ pé Ọlọ́run kò ní. Ipa wo làwọn ànímọ́ wọ̀nyí ní lórí gbogbo ẹni tó nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run tó sì fara mọ́ ìṣàkóso rẹ̀? Họ́wù, ọ̀nà tí Jèhófà gbà ń fi ìwà rere àti òdodo ṣàkóso ń mú ayọ̀ wá fún àwọn olùjọ́sìn rẹ̀ débi pé wọn ò lè ṣe kí wọ́n má máa fi ọ̀yàyà yìn ín. Ìyẹn nìkan kọ́ o, oore Jèhófà tún nasẹ̀ dé ọ̀dọ̀ ‘gbogbo èèyàn.’ A lérò pé èyí yóò ran ọ̀pọ̀ èèyàn lọ́wọ́ láti ronú pìwà dà, kí wọ́n sì di olùjọsìn Ọlọ́run tòótọ́ náà kó tó pẹ́ jù.—Ìṣe 14:15-17.
22. Báwo ni Jèhófà ṣe ń bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lò?
22 Dáfídì tún mọyì àwọn ànímọ́ tí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ fi hàn nígbà tí Ọlọ́run “kọjá níwájú [Mósè] ní pípolongo pé: ‘Jèhófà, Jèhófà, Ọlọ́run aláàánú àti olóore ọ̀fẹ́, ó ń lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ yanturu ní inú-rere-onífẹ̀ẹ́ àti òtítọ́.’” (Ẹ́kísódù 34:6) Abájọ tí Dáfídì fúnra rẹ̀ fi polongo pé: “Jèhófà jẹ́ olóore ọ̀fẹ́ àti aláàánú, Ó ń lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní inú-rere-onífẹ̀ẹ́.” Bó tilẹ̀ jẹ́ pé títóbi Jèhófà jẹ́ àwámáridìí, síbẹ̀ ó ka àwọn èèyàn tó jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ sí nípa fífi ìyọ́nú bá wọn lò. Ó kún fún àánú, ó sì múra tán láti dárí ji àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ tó bá ronú pìwà dà lórí ìpìlẹ̀ ẹbọ ìràpadà Jésù. Jèhófà tún máa ń lọ́ra láti bínú, ìdí nìyẹn tó fi fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ láǹfààní láti ṣẹ́pá àwọn ìkùdíẹ̀-káàtó tó lè dí wọn lọ́wọ́ wíwọnú ayé tuntun òdodo rẹ̀.—2 Pétérù 3:9, 13, 14.
-
-
Inú-rere-onífẹ̀ẹ́ Jèhófà Mà Pọ̀ O!Ilé Ìṣọ́—2004 | January 15
-
-
Inú-rere-onífẹ̀ẹ́ Jèhófà Mà Pọ̀ O!
“Jèhófà . . . pọ̀ ní inú-rere-onífẹ̀ẹ́.”—SÁÀMÙ 145:8.
1. Ibo ni ìfẹ́ Ọlọ́run nasẹ̀ dé?
“ỌLỌ́RUN jẹ́ ìfẹ́.” (1 Jòhánù 4:8) Gbólóhùn amọ́kànyọ̀ yìí fi hàn pé ìfẹ́ ni Jèhófà fi ń ṣàkóso. Àní, àwọn tí kò ṣègbọràn sí i pàápàá ń gbádùn oòrùn àti òjò tó ń fìfẹ́ pèsè! (Mátíù 5:44, 45) Kódà ìfẹ́ tí Ọlọ́run ní fún aráyé yìí lè mú káwọn ọ̀tá rẹ̀ pàápàá ronú pìwà dà, kí wọ́n yí padà sọ́dọ̀ rẹ̀, kí wọ́n sì ní ìyè àìnípẹ̀kun. (Jòhánù 3:16) Àmọ́ ṣá o, láìpẹ́ Jèhófà yóò pa gbogbo àwọn ẹni ibi tó bá kọ̀ láti ronú pìwà dà run, káwọn èèyàn tó nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ lè gbádùn ìyè àìnípẹ̀kun nínú ayé tuntun òdodo.—Sáàmù 37:9-11, 29; 2 Pétérù 3:13.
2. Irú ìfẹ́ àrà ọ̀tọ̀ wo ni Jèhófà fi hàn sáwọn tó ya ara wọn sí mímọ́ fún un?
2 Jèhófà fi ìfẹ́ àrà ọ̀tọ̀ tí kò lópin hàn sáwọn olùjọsìn rẹ̀ tòótọ́. Irú ìfẹ́ bẹ́ẹ̀ la fi ọ̀rọ̀ Hébérù tá a túmọ̀ sí “inú-rere-onífẹ̀ẹ́” tàbí “ìfẹ́ dídúróṣinṣin” ṣàpèjúwe. Dáfídì Ọba Ísírẹ́lì ìgbàanì mọyì inú-rere-onífẹ̀ẹ́ tí Ọlọ́run ní yìí gidigidi. Ohun tójú Dáfídì alára ti rí àti àṣàrò tó ti ṣe lórí ọ̀nà tí Ọlọ́run gbà ń bá àwọn èèyàn lò mú kó kọrin láìmikàn pé: “Jèhófà . . . pọ̀ ní inú-rere-onífẹ̀ẹ́ [tàbí, “ìfẹ́ dídúróṣinṣin”].”—Sáàmù 145:8.
-