ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹtì Àwọn Ẹlẹ́kọ̀ọ́ Ìsìn
    Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | March 1
    • Ìwé Catechism of the Catholic Church sọ pé: “Láti lè jíǹde pẹ̀lú Kristi, a gbọ́dọ̀ kú pẹ̀lú Kristi: a gbọ́dọ̀ ‘ti inú ara wa kúrò, kí a sì lè wà ní ilé lọ́dọ̀ Oluwa’. [2 Korinti 5:8] Nígbà ‘lílọ’ yẹn tí ó jẹ́ ikú a ń ya ọkàn nípa kúrò lọ́dọ̀ ara. [Filippi 1:23] A óò so ò pọ̀ ṣọ̀kan pẹ̀lú ara ní ọjọ́ àjíǹde àwọn òkú.” Ṣùgbọ́n nínú àwọn ẹsẹ tí a fàyọ níhìn-ín, aposteli Paulu ha sọ pé ọkàn ń la ikú ara já tí ó sì ń dúró de “Ìdájọ́ Ìkẹyìn” láti lè tún padà wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ara bí?

  • Ẹtì Àwọn Ẹlẹ́kọ̀ọ́ Ìsìn
    Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | March 1
    • Ní Filippi 1:21, 23, (NW) Paulu sọ pé: “Ninu ọ̀ràn mi lati wà láàyè jẹ́ Kristi, ati lati kú, èrè. Mo wà lábẹ́ ìkìmọ́lẹ̀ lọ́wọ́ awọn ohun méjì wọnyi; ṣugbọn ohun tí mo ní ìfẹ́-ọkàn sí ni ìtúsílẹ̀ ati wíwà pẹlu Kristi, nitori, láìsí àní-àní, èyí sàn púpọ̀púpọ̀ jù.” Paulu ha ń sọ̀rọ̀ nípa “ipò agbedeméjì” níhìn-ín bí? Àwọn kan rò bẹ́ẹ̀. Bí ó ti wù kí ó rí, Paulu sọ pé àwọn ohun méjì tí ó ṣeé ṣe kí ó fi òun sábẹ́ ìkìmọ́lẹ̀ ni—ìyè tàbí ikú. Ó fikún un, ní mímẹ́nuba ohun kẹta tí ó lè mú kí ó ṣeé ṣe, “Ṣugbọn ohun ti mo ni ìfẹ́-ọkàn sí ni ìtúsílẹ̀ ati wíwà pẹlu Kristi.” “Ìtúsílẹ̀” láti wà papọ̀ pẹ̀lú Kristi kété lẹ́yìn ikú ha ni bí? Ó dára, gẹ́gẹ́ bí a ti rí i ṣáájú, Paulu gbàgbọ́ pé àwọn Kristian olùṣòtítọ́ tí wọ́n jẹ́ ẹni-àmì-òróró ni a óò jíǹde nígbà wíwà níhìn-ín Kristi. Nítorí náà, ó níláti ní àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ àkókò yẹn lọ́kàn.

      Èyí ni a lè rí nínú àwọn ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí a rí ní Filippi 3:20, 21 àti 1 Tessalonika 4:16. Irú “ìtúsílẹ̀” bẹ́ẹ̀ nígbà wíwà níhìn-ín Kristi Jesu yóò mú kí ó ṣeé ṣe fún Paulu láti gba èrè náà tí Ọlọrun ti pèsè sílẹ̀ fún un. Òtítọ́ náà pé èyí ni ìrètí rẹ̀ ni a rí nínú àwọn ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí ọ̀dọ́mọkùnrin náà Timoteu pé: “Lati àkókò yii lọ a ti fi adé òdodo pamọ́ dè mí, èyí tí Oluwa, onídàájọ́ òdodo, yoo fún mi gẹ́gẹ́ bí èrè-ẹ̀san ní ọjọ́ yẹn, síbẹ̀ kì í ṣe fún emi nìkan, ṣugbọn fún gbogbo awọn wọnnì tí wọ́n ti nífẹ̀ẹ́ ìfarahàn kedere rẹ̀ pẹlu.”—2 Timoteu 4:8, NW.

Yorùbá Publications (1987-2026)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2026 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́