-
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn ÒǹkàwéIlé Ìṣọ́—2001 | October 1
-
-
Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ̀wé sáwọn Hébérù tó jẹ́ Kristẹni ní ọ̀rúndún kìíní pé: “Ìsinmi ti sábáàtì kan ṣì kù fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run. Nítorí ẹni tí ó ti wọnú ìsinmi Ọlọ́run, òun pẹ̀lú ti sinmi kúrò nínú àwọn iṣẹ́ tirẹ̀, gan-an gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti ṣe kúrò nínú tirẹ̀. Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí a sa gbogbo ipá wa láti wọnú ìsinmi yẹn.”—Hébérù 4:9-11.
-
-
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn ÒǹkàwéIlé Ìṣọ́—2001 | October 1
-
-
Táa bá padà lọ wo ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù sọ nínú Hébérù, a óò rí i pé ó tọ́ka sí i pé “ìsinmi sábáàtì kan ṣì kù fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run,” ó sì rọ àwọn Kristẹni ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ pé kí wọ́n sa gbogbo ipá wọn “láti wọnú ìsinmi yẹn.” Èyí fi hàn pé nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń kọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyẹn, “ọjọ́ keje” ìsinmi Ọlọ́run, tó bẹ̀rẹ̀ ní nǹkan bí ẹgbẹ̀rún mẹ́rin [4,000] ọdún ṣáájú ìgbà yẹn, ṣì ń lọ lọ́wọ́. Kó tó di pé ó dópin, gbogbo ète Ọlọ́run fún aráyé àti ilẹ̀ ayé ti gbọ́dọ̀ nímùúṣẹ pátápátá ní òpin Ẹgbẹ̀rún Ọdún Ìjọba Jésù Kristi, tí í ṣe “Olúwa sábáàtì.”—Mátíù 12:8; Ìṣípayá 20:1-6; 21:1-4.
-
-
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn ÒǹkàwéIlé Ìṣọ́—2001 | October 1
-
-
Ó dájú pé ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù sọ nípa ìsinmi Ọlọ́run àti béèyàn ṣe lè wọnú rẹ̀ jẹ́ orísun ìṣírí fáwọn Hébérù tó jẹ́ Kristẹni tí ń gbé ní Jerúsálẹ́mù, àwọn tó ti fàyà rán ọ̀pọ̀ inúnibíni àti ìfiniṣẹ̀sín nítorí ìgbàgbọ́ wọn. (Ìṣe 8:1; 12:1-5) Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù lè jẹ́ orísun ìṣírí fún àwa Kristẹni òde òní. Níwọ̀n bí a ti rí i pé ìlérí Ọlọ́run nípa párádísè orí ilẹ̀ ayé lábẹ́ Ìjọba òdodo rẹ̀ kò ní pẹ́ ní ìmúṣẹ, àwa pẹ̀lú yóò sinmi kúrò nínú iṣẹ́ tara wa, a ó sì máa sa gbogbo ipá wa láti wọnú ìsinmi yẹn.—Mátíù 6:10, 33; 2 Pétérù 3:13.
-