-
Ìṣe 28:17-19Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
17 Àmọ́, ọjọ́ mẹ́ta lẹ́yìn náà, Pọ́ọ̀lù pe àwọn sàràkí-sàràkí jọ lára àwọn Júù. Nígbà tí wọ́n pé jọ, ó sọ fún wọn pé: “Ẹ̀yin èèyàn, ẹ̀yin ará, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mi ò ṣe ohunkóhun tó lòdì sí àwọn èèyàn tàbí sí àṣà àwọn baba ńlá wa,+ síbẹ̀ wọ́n fà mí lé ọwọ́ àwọn ará Róòmù ní ẹlẹ́wọ̀n láti Jerúsálẹ́mù.+ 18 Lẹ́yìn tí wọ́n ṣe àyẹ̀wò,+ wọ́n fẹ́ dá mi sílẹ̀, nítorí kò sí ìdí kankan tó fi yẹ kí wọ́n pa mí.+ 19 Àmọ́ nígbà tí àwọn Júù fárí gá, ó di dandan fún mi láti ké gbàjarè sí Késárì,+ ṣùgbọ́n kì í ṣe torí pé mo ní ẹ̀sùn tí mo fẹ́ fi kan orílẹ̀-èdè mi.
-