5 Ẹ̀yin ẹrú, ẹ máa gbọ́ràn sí àwọn ọ̀gá yín* lẹ́nu,+ pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìwárìrì nínú òótọ́ ọkàn, gẹ́gẹ́ bíi sí Kristi, 6 kì í ṣe nígbà tí wọ́n bá ń wò yín nìkan, torí kí ẹ lè tẹ́ èèyàn lọ́rùn,*+ àmọ́ bí ẹrú Kristi, tó ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run tọkàntọkàn.*+
9 Kí àwọn ẹrú máa tẹrí ba fún àwọn ọ̀gá wọn nínú ohun gbogbo,+ kí wọ́n máa ṣe gbogbo ohun tí wọ́n lè ṣe láti tẹ́ wọn lọ́rùn, kí wọ́n má sì gbó wọn lẹ́nu,
18 Kí àwọn ìránṣẹ́ máa tẹrí ba fún àwọn ọ̀gá wọn pẹ̀lú ìbẹ̀rù tó yẹ,+ kì í ṣe fún àwọn tó jẹ́ ẹni rere, tó sì ń gba tẹni rò nìkan, àmọ́ fún àwọn tó ṣòroó tẹ́ lọ́rùn pẹ̀lú.