ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Kọ́ríńtì 2:9, 10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Àmọ́, bó ṣe wà lákọsílẹ̀ pé: “Ojú kò tíì rí, etí kò sì tíì gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn èèyàn kò tíì ro àwọn ohun tí Ọlọ́run ti pèsè sílẹ̀ fún àwọn tó nífẹ̀ẹ́ rẹ̀.”+ 10 Nítorí àwa ni Ọlọ́run ti ṣí wọn payá fún+ nípasẹ̀ ẹ̀mí rẹ̀,+ nítorí ẹ̀mí ń wá inú ohun gbogbo, títí kan àwọn ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run.+

  • Éfésù 1:9-12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 bó ṣe jẹ́ ká mọ àṣírí mímọ́+ nípa ìfẹ́ rẹ̀. Èyí bá ohun tó ń wù ú mu, ó sì tipa bẹ́ẹ̀ ṣètò 10 iṣẹ́ àbójútó kan* láti kó ohun gbogbo jọ nínú Kristi nígbà tí àwọn àkókò tí a yàn bá tó, àwọn ohun tó wà ní ọ̀run àti àwọn ohun tó wà ní ayé.+ Bẹ́ẹ̀ ni, nínú ẹni 11 tí a wà níṣọ̀kan pẹ̀lú rẹ̀, tí a sì yàn wá láti jẹ́ ajogún pẹ̀lú rẹ̀,+ ní ti pé a ti yàn wá ṣáájú nítorí ohun tí ẹni tó ń ṣe ohun gbogbo fẹ́, bí ó ṣe ń pinnu ohun tó bá ìfẹ́ rẹ̀ mu, 12 kí iṣẹ́ ìsìn àwa tí a kọ́kọ́ nírètí nínú Kristi lè yìn ín lógo.

  • Kólósè 1:26, 27
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 26 àṣírí mímọ́+ tí a fi pa mọ́ láti àwọn ètò àwọn nǹkan* tó ti kọjá+ àti láti àwọn ìran tó ti kọjá. Àmọ́ ní báyìí, a ti fi han àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀,+ 27 ìyẹn àwọn tó wu Ọlọ́run pé kí wọ́n mọ ọrọ̀ ológo nípa àṣírí mímọ́ yìí láàárín àwọn orílẹ̀-èdè,+ àṣírí yìí ni Kristi tó wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú yín, ìyẹn ìrètí ògo rẹ̀.+

Yorùbá Publications (1987-2026)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2026 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́